Publicidade

Cânticos 6

Ọ̀rẹ́

1 Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,

ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?

Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,

kí a lè bá ọ wá a?

Olólùfẹ́

2 Olùfẹ́ mi ti sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ọgbà rẹ̀,

sí ibi ibùsùn tùràrí,

láti máa jẹ nínú ọgbà

láti kó ìtànná lílì jọ.

3 Èmi ni ti olùfẹ́ mi, olùfẹ́ mi sì ni tèmi,

Ó ń jẹ láàrín ìtànná lílì.

Olùfẹ́

4 Ìwọ lẹ́wà olùfẹ́ mi, bí i Tirsa,

ìwọ lẹ́wà bí i Jerusalẹmu,

ìwọ ògo bí ogun pẹ̀lú ọ̀págun.

5 Yí ojú rẹ kúrò lára mi;

nítorí ojú rẹ borí mi.

Irun rẹ rí bí i ọ̀wọ́ ewúrẹ́

tí ó sọ̀kalẹ̀ wá láti Gileadi.

6 Eyín rẹ rí bí ọ̀wọ́ àgùntàn,

tí ó gòkè láti ibi ìwẹ̀ rẹ̀ wá,

gbogbo wọn bí ìbejì,

kò sì ṣí ọ̀kankan tí ó yàgàn nínú wọn.

7 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ lẹ́bàá ìbòjú rẹ,

rí bí ẹ̀là èso pomegiranate.

8 Ọgọ́ta ayaba ní ń bẹ níbẹ̀,

àti ọgọ́rin àlè,

àti àwọn wúńdíá láìníye.

9 Àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi, ọ̀kan ni,

ọ̀kan ṣoṣo ọmọbìnrin ìyá rẹ̀,

ààyò ẹyọ kan ṣoṣo ẹni tí ó bí i.

Àwọn obìnrin rí i wọ́n pè é ní alábùkún fún

àwọn ayaba àti àwọn àlè gbé oríyìn fún un.

Ọ̀rẹ́

10 Ta ni èyí tí ó tàn jáde bí i ìràwọ̀ òwúrọ̀,

tí ó dára bí òṣùpá, tí ó mọ́lẹ̀ bí oòrùn,

tí ó ní ẹ̀rù bí i jagunjagun pẹ̀lú ọ̀págun?

Olùfẹ́

11 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ọgbà èso igi

láti wo àwọn ẹ̀ka igi tuntun ní àfonífojì,

láti rí i bí àjàrà rúwé,

tàbí bí pomegiranate ti rudi.

12 Kí èmi tó mọ̀,

àárẹ̀ ọkàn mú mi, mo sì fẹ́ kí ń wà láàrín àwọn ènìyàn mi.

Ọ̀rẹ́

13 Padà wá, padà wá, ìwọ ọmọ Ṣulamati;

padà wá, padà wá, kí àwa kí ó lè yọ́ ọ wò.

Olùfẹ́

Èéṣe tí ẹ̀yin fẹ́ yọ́ Ṣulamati wò,

bí ẹni pé orin ijó Mahanaimu?

Veja também

Publicidade
Cânticos
Ver todos os capítulos de Cânticos
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-