Publicidade

Provérbios 17

1 Òkèlè gbígbẹ tòun tàlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ sàn

ju ilé tí ó kún fọ́fọ́ fún ẹran àti ìjà.

2 Ọlọ́gbọ́n ìránṣẹ́ yóò ṣàkóso adójútini ọmọ,

yóò sì pín ogún gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ.

3 Iná ni a fi fọ́ fàdákà àti wúrà,

ṣùgbọ́n Olúwa ló ń dán ọkàn wò.

4 Ènìyàn búburú ń tẹ́tí sí ètè tí ń sọ ibi;

òpùrọ́ a máa fetí sí ahọ́n búburú.

5 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sín olùpọ́njú jẹ, ó gan Ẹlẹ́dàá rẹ̀,

ẹnikẹ́ni tí ń yọ̀ sí ìyọnu kò ní lọ láìjìyà.

6 Ọmọ ọmọ ni adé orí arúgbó,

ògo àwọn ọmọ sì ni òbí jẹ.

7 Ọ̀rọ̀ dídùn kò yẹ aṣiwèrè,

bẹ́ẹ̀ ni ètè èké kò yẹ ọmọ-aládé!

8 Òkúta iyebíye jẹ́ ẹ̀bùn ní ojú ẹni tí ó ni í,

ibikíbi tí ó yí sí, á ṣe rere.

9 Ẹni tí ó fojú fo ẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n ṣẹ̀ ẹ́ mú kí ìfẹ́ gbòòrò sí i.

Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ń tẹnumọ́ ọ̀rọ̀ yóò pín ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ méjì ní yà.

10 Ọ̀rọ̀ ìbáwí dun olóye ènìyàn

ju ọgọ́rùn-ún pàṣán lọ lẹ́yìn òmùgọ̀.

11 Orí kunkun ni ènìyàn ìkà máa ń ṣe,

ìjòyè aláìláàánú ni a ó rán sí i.

12 Ó sàn kí ènìyàn pàdé beari tí a ti kó lọ́mọ

jù aláìgbọ́n nínú ìwà òmùgọ̀ rẹ̀.

13 Bí ènìyàn kan bá fi ibi san ìre,

ibi kì yóò kúrò nílé rẹ̀ láéláé.

14 Bíbẹ̀rẹ̀ ìjà dàbí ẹni tí ó dá ojú fún adágún omi;

nítorí náà mẹ́nu kúrò nínú ọ̀rọ̀ kí ó tó di ìjà.

15 Gbígbé ẹ̀bi fún aláre àti dídá ẹni jàre lẹ́bi,

Olúwa kórìíra méjèèjì.

16 Kí ni ìwúlò owó lọ́wọ́ aṣiwèrè,

níwọ̀n bí kò ti ní èròǹgbà láti rí ọgbọ́n?

17 Ọ̀rẹ́ a máa fẹ́ni nígbà gbogbo,

arákùnrin sì wà fún ìgbà ìpọ́njú.

18 Ènìyàn aláìgbọ́n ṣe ìbúra,

ó sì ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ̀.

19 Ẹni tí ó fẹ́ràn ìjà fẹ́ràn ẹ̀ṣẹ̀;

ẹni tí ó kọ́ ibodè gígàn ń wá ìparun.

20 Ènìyàn aláyídáyidà ọkàn kì í gbèrú,

ẹni tí ó ní ahọ́n ẹ̀tàn bọ́ sínú ìyọnu.

21 Láti bí aláìgbọ́n lọ́mọ a máa fa ìbànújẹ́ ọkàn,

kò sí ayọ̀ fún baba ọmọ tí kò gbọ́n.

22 Ọkàn tí ó túká jẹ́ oògùn gidi,

ṣùgbọ́n ọkàn tí ó bàjẹ́ a máa mú kí egungun gbẹ.

23 Ènìyàn búburú a gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀

láti yí ìdájọ́ po.

24 Olóye ènìyàn gbójú wo ọgbọ́n níwájú,

ṣùgbọ́n ojú aláìgbọ́n ń wò káàkiri ilẹ̀ ayé.

25 Aṣiwèrè ọmọ mú ìbànújẹ́ bá baba rẹ̀

àti ìkorò fún ẹni tí ó bí i lọ́mọ.

26 Kò dára láti fìyà jẹ ènìyàn tí kò ṣẹ̀,

tàbí láti na ìjòyè lórí òtítọ́ inú wọn.

27 Ènìyàn tó ní ìmọ̀ máa ń ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ń sọ,

ènìyàn olóye sì máa ń ní sùúrù.

28 Kódà aláìgbọ́n máa ń dàbí ọlọ́gbọ́n bí ó bá dákẹ́,

àti bí olóye bí ó bá fètèmétè.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-