Publicidade

Amós 3

Ẹ̀rí jíjẹ́ nípa àwọn ọmọ Israẹli

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:

2 "Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn

nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí;

nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà

fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ."

3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀

láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?

4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó,

bí kò bá ní ohun ọdẹ?

Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀

bí kò bá rí ohun kan mú?

5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀

nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un?

Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀

nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?

6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú,

àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù?

Tí ewu bá wa lórí ìlú

kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?

7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan

láìfi èrò rẹ̀ hàn

fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.

8 Kìnnìún ti bú ramúramù

ta ni kì yóò bẹ̀rù?

Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀

ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?

9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu

àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti.

"Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria;

kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀

àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ."

10 "Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere," ni Olúwa wí,

"àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀."

11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

"Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;

yóò wó ibi gíga yín palẹ̀

a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́."

12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

"Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì

kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan

bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli,

tí ń gbé Samaria kúrò

ní igun ibùsùn wọn

ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku."

13 "Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu," ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

14 "Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run;

ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò

yóò sì wó lulẹ̀.

15 Èmi yóò wó ilé òtútù

lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru;

ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé

a ó sì pa ilé ńlá náà run,"

ni Olúwa wí.

Veja também

Publicidade
Amós
Ver todos os capítulos de Amós
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-