Publicidade

Provérbios 12

1 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kórìíra ìbáwí jẹ́ aláìgbọ́n.

2 Ènìyàn rere gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa

ṣùgbọ́n ènìyàn ètè búburú ni yóò dá lẹ́bi.

3 A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburú

ṣùgbọ́n a kò le è fa olódodo tu.

4 Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀

ṣùgbọ́n aya adójútini dàbí inú egungun rẹ̀ jẹrà.

5 Èrò àwọn olódodo tọ́,

ṣùgbọ́n ìgbìmọ̀ ènìyàn búburú jẹ́ ẹ̀tàn.

6 Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀

ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ àwọn olódodo gbà wọ́n là.

7 A ṣí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́;

ṣùgbọ́n ilé olódodo dúró ṣinṣin.

8 A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀

ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.

9 Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́

ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láìní oúnjẹ.

10 Olódodo ènìyàn ń ṣe aájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílò,

ṣùgbọ́n ìyọ́nú àwọn ènìyàn búburú, ìkà ni.

11 Ẹni tí ó bá dá oko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,

ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásán làsàn kò gbọ́n.

12 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógun àwọn ènìyàn ìkà

ṣùgbọ́n gbòǹgbò olódodo ń gbilẹ̀.

13 A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀

ṣùgbọ́n olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdààmú.

14 Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rere

bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.

15 Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀

ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.

16 Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀,

ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.

17 Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí òtítọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ rí

ṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.

18 Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀

ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọ́gbọ́n ń mú ìwòsàn wá.

19 Ètè tí ń ṣọ òtítọ́ yóò wà láéláé

ṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.

20 Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburú

ṣùgbọ́n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.

21 Ibi kì í ṣubú lu olódodo rárá

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.

22 Olúwa kórìíra ètè tí ń parọ́

ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn olóòtítọ́.

23 Ènìyàn olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀

ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.

24 Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jẹ ọba

ṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí ẹrú ṣíṣe.

25 Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodò

ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.

26 Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́

ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn ṣìnà.

27 Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹ

ṣùgbọ́n ẹni tí kì í ṣe ọ̀lẹ máa ń díwọ̀n ohun ìní rẹ̀.

28 Ní ọ̀nà àwọn olódodo ni ìyè wà

ní ọ̀nà náà ni àìkú wà.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-