Publicidade

Provérbios 27

1 Má ṣe yangàn nítorí ọ̀la

nítorí o kò mọ ohun tí ọjọ́ kan le è mú wáyé.

2 Jẹ́ kí ẹlòmíràn yìn ọ́ dípò ẹnu ara rẹ,

àní àlejò, kí ó má sì ṣe ètè ìwọ fúnra rẹ̀.

3 Òkúta wúwo, erùpẹ̀ sì wúwo

ṣùgbọ́n ìbínú aṣiwèrè wúwo ju méjèèjì lọ.

4 Ìbínú ni ìkà, ìrunú sì burú púpọ̀

ṣùgbọ́n ta ni ó le è dúró níwájú owú?

5 Ìbániwí gbangba sàn

ju ìfẹ́ ìkọ̀kọ̀ lọ.

6 Òtítọ́ ni ọgbẹ́ ọ̀rẹ́,

ṣùgbọ́n ìfẹnukonu ọ̀tá ni ẹ̀tàn.

7 Kódà oyin kò dùn lẹ́nu ẹni tí ó ti yó

ṣùgbọ́n òróǹró gan an dùn lẹ́nu ẹni tí ebi ń pa.

8 Bí ẹyẹ tí ó ṣáko lọ kúrò níbi ìtẹ́ rẹ̀

ni ènìyàn tí ó ṣáko lọ kúrò ní ilé rẹ̀.

9 Ìpara olóòórùn dídùn àti tùràrí ń mú ayọ̀ wá sínú ọkàn

bẹ́ẹ̀ ni inú dídùn láti ọ̀dọ̀ ọ̀rẹ́ ń wá láti inú ìmọ̀ràn tí ó ṣàkóso.

10 Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,

má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdààmú dé bá ọ

ó sàn kí o jẹ́ aládùúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà sí ni.

11 Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn mi

nígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.

12 Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fi ara pamọ́

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí, kàkà kí ó dúró ó tẹ̀síwájú, ó sì jìyà rẹ̀.

13 Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjèjì

fi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oníṣekúṣe.

14 Bí ènìyàn kan ń kígbe súre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀

a ó kà á sí bí èpè.

15 Àyà tí ó máa ń jà dàbí

ọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;

16 dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kun

tàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.

17 Bí irin tí ń pọ́n irin mú

bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.

18 Ẹni tí ó tọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ yóò jẹ èso rẹ̀

ẹni tí ó sì fojú tó ọ̀gá rẹ̀ yóò gba ọlá.

19 Bí omi tí ń ṣe àfihàn ojú, nígbà tí a bá wò ó

bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ènìyàn ń ṣe àfihàn ènìyàn.

20 Kò tẹ́ ikú àti ìparun lọ́rùn rí

bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ni ojú ènìyàn kò rí ìtẹ́lọ́rùn rí.

21 Iná fún fàdákà iná ìléru fún wúrà,

ṣùgbọ́n a ń dán ènìyàn wò nípa ìyìn tí ó ń gbà.

22 Bí a tilẹ̀ gún aláìgbọ́n nínú odó,

fi ọmọ odó gún un bí èlùbọ́

ìwọ kì yóò le è yọ ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ kúrò ní inú rẹ̀.

23 Rí i dájú pé o mọ ipò tí àwọn agbo àgùntàn rẹ wà

bojútó àwọn agbo màlúù rẹ dáradára;

24 nítorí ọrọ̀ kì í pẹ́ lọ títí

adé kì í sì í wà lórí títí láéláé.

25 Nígbà tí a bá kó koríko, ewéko tuntun yóò sì hù jáde, a ó sì kó koríko àwọn orí òkè wọlé

26 àwọn àgùntàn yóò pèsè aṣọ fún ọ,

àti ewúrẹ́ yóò pèsè owó oko.

27 Ìwọ yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà ewúrẹ́

láti bọ́ ọ àti ìdílé rẹ

àti láti tọ́jú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-