Publicidade

Provérbios 8

Ọgbọ́n n fi ìpè síta

1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?

Òye kò ha ń gbé ohùn rẹ sókè?

2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà,

ní ìkóríta, ní ó dúró;

3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,

ní ẹnu ibodè ni ó ń kígbe sókè:

4 "Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;

mo gbé ohun mi sókè sí gbogbo ènìyàn.

5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;

ẹ̀yin aṣiwèrè, ẹ gba òye.

6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;

Èmí ṣí ètè mi láti sọ ohun tí ó tọ́,

7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,

nítorí ètè mi kórìíra ibi.

8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,

kò sí èyí tí ó jẹ́ ẹ̀tàn tàbí àyídáyidà níbẹ̀.

9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;

wọ́n jẹ́ aláìlẹ́gàn fún gbogbo ẹni tí ó ní ìmọ̀.

10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,

ìmọ̀ dípò o wúrà àṣàyàn,

11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,

kò sí ohun tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ tí a sì le fiwé e.

12 "Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;

mo ní ìmọ̀ àti ọgbọ́n-inú.

13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi

mo kórìíra ìgbéraga àti agídí,

ìwà ibi àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.

14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi

mo ní òye àti agbára.

15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso

tí àwọn aláṣẹ sì ń ṣe òfin tí ó dára.

16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso,

àti gbogbo ọlọ́lá tí ń ṣàkóso ilẹ̀ ayé.

17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi,

àwọn tí ó sì wá mi rí mi.

18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà,

ọrọ̀ tí í tọ́jọ́ àti ìgbéga rere.

19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;

ohun tí mò ń mú wá ju àṣàyàn fàdákà lọ.

20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,

ní ojú ọ̀nà òtítọ́,

21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi

mo sì ń mú kí ilé ìṣúra wọn kún.

22 "Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.

Ṣáájú àwọn iṣẹ́ rẹ̀ àtijọ́;

23 a ti yàn mí láti ayérayé,

láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, kí ayé tó bẹ̀rẹ̀.

24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi,

nígbà tí kò tí ì sí ìsun tí ó ní omi nínú;

25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,

ṣáájú àwọn òkè ni a ti bí mi,

26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀

tàbí èyíkéyìí nínú eruku ayé.

27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,

nígbà tí ó fi òsùwọ̀n àyíká sórí ibú omi,

28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè

tí ó sì fi orísun ibú omi sí ipò rẹ̀ láì le è yẹsẹ̀,

29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun

kí omi má ba à kọjá ààlà àṣẹ rẹ̀,

àti nígbà tí ó pààlà ìpìlẹ̀ ayé.

30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀

mo kún fún inú dídùn lójoojúmọ́,

mo ń yọ̀ nígbà gbogbo níwájú rẹ̀.

31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá

mo sì ní inú dídùn sí àwọn ọmọ ènìyàn.

32 "Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,

ìbùkún ni fún àwọn tí ó pa ọ̀nà mi mọ́.

33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;

má ṣe pa á tì sápá kan.

34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,

tí ń ṣọ́nà ní ẹnu-ọ̀nà mi lójoojúmọ́,

tí ń dúró ní ẹnu-ọ̀nà mi.

35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè

ó sì rí ojúrere gbà lọ́dọ̀ Olúwa.

36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára

gbogbo ẹni tí ó kórìíra mi fẹ́ ikú."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-