Publicidade

Provérbios 18

1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀;

ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.

2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye

ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.

3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé,

nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.

4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn,

ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.

5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú

tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.

6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀

ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.

7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́,

ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.

8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn;

wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.

9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀

arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.

10 Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni;

olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.

11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn;

wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.

12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga,

ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.

13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́,

èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.

14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn,

ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.

15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;

etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.

16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn

a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.

17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre,

títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.

18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà

a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.

19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ,

ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.

20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó;

láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.

21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn,

àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.

22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere,

o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.

23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú,

ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.

24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun,

ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-