Publicidade

Cânticos 3

1 Ní orí ibùsùn mi ní òru

mo wá ẹni tí ọkàn mí fẹ́;

mo wá a, ṣùgbọ́n èmi kò rí i.

2 Èmi yóò dìde nísinsin yìí, èmi yóò sì rìn lọ káàkiri ìlú,

ní àwọn òpópónà àti ní àwọn gbangba òde;

èmi yóò wá ẹni tí ọkàn mi fẹ́.

Bẹ́ẹ̀ ni mo wá a ṣùgbọ́n èmi kò rí i.

3 Àwọn ọdẹ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi

bí wọ́n ṣe ń rìn yíká ìlú.

"Ǹjẹ́ ìwọ ti rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́?"

4 Gẹ́rẹ́ tí mo fi wọ́n sílẹ̀

ni mo rí ẹni tí ọkàn mi fẹ́.

Mo dìímú, èmi kò sì jẹ́ kí ó lọ

títí tí mo fi mú u wá sílé ìyá mi,

sínú yàrá ẹni tí ó lóyún mi.

5 Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,

mo fi àwọn abo egbin àti abo àgbọ̀nrín igbó fi yín bú

kí ẹ má ṣe rú olùfẹ́ mi sókè

kí ẹ má sì ṣe jí i títí yóò fi wù ú.

6 Ta ni ẹni tí ń ti ijù jáde wá

bí ọ̀wọ̀n èéfín

tí a ti fi òjìá àti tùràrí kùn lára

pẹ̀lú gbogbo ìpara olóòórùn oníṣòwò?

7 Wò ó! Àkéte rẹ̀ tí í ṣe ti Solomoni,

àwọn akọni ọgọ́ta ni ó wà yí i ká,

àwọn akọni Israẹli,

8 gbogbo wọn ni ó mú idà lọ́wọ́,

gbogbo wọn ní ìmọ̀ nínú ogun,

idà oníkálùkù wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀,

wọ́n múra sílẹ̀ fún ìdágìrì òru

9 Solomoni ọba ṣe àkéte fún ara rẹ̀;

o fi igi Lebanoni ṣe é.

10 Ó fi fàdákà ṣe òpó rẹ̀,

o fi wúrà ṣe ibi ẹ̀yìn rẹ̀.

Ó fi elése àlùkò ṣe ibùjókòó rẹ̀,

inú rẹ̀ ni ó ko àwọn ọ̀rọ̀ ìfẹ́ wọ̀nyí sí.

"Pẹ̀lú ìfẹ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Jerusalẹmu."

11 Ẹ jáde wá, ẹ̀yin ọmọbìnrin Sioni,

kí ẹ sì wo ọba Solomoni tí ó dé adé,

adé tí ìyá rẹ̀ fi dé e

ní ọjọ́ ìgbéyàwó rẹ̀,

ní ọjọ́ ayọ̀ ọkàn rẹ̀.

Veja também

Publicidade
Cânticos
Ver todos os capítulos de Cânticos
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-