Publicidade

Isaías 46

Àwọn Ọlọ́run Babeli

1 Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀;

àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù.

Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di

àjàgà sí wọn lọ́rùn,

ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.

2 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀;

wọn kò lè gba ẹrù náà,

àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.

3 "Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu,

gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli,

ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún,

tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.

4 Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín,

Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró.

Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ;

Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.

5 "Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba?

Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi

tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?

6 Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn

wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n;

wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà,

wọn sì tẹríba láti sìn ín.

7 Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n,

wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí.

Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà.

Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn;

òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.

8 "Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ,

fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.

9 Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́;

Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn;

Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.

10 Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá,

láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá.

Mo wí pé, Ète mi yóò dúró,

àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.

11 Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá;

láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ.

Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ;

èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.

12 Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn,

ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.

13 Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí,

kò tilẹ̀ jìnnà rárá;

àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró.

Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà

ògo mi fún Israẹli.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-