Publicidade

Isaías 52

1 Jí, jí, ìwọ Sioni,

wọ ara rẹ ní agbára.

Gbé aṣọ ògo rẹ wọ̀,

ìwọ Jerusalẹmu, ìlú mímọ́ n nì.

Àwọn aláìkọlà àti aláìmọ́

kì yóò wọ inú rẹ mọ́.

2 Gbọn eruku rẹ kúrò;

dìde sókè, kí o sì gúnwà, ìwọ Jerusalẹmu.

Bọ́ ẹ̀wọ̀n tí ń bẹ lọ́rùn rẹ kúrò,

ìwọ ọ̀dọ́mọbìnrin ìgbèkùn Sioni.

3 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí,

"Ọ̀fẹ́ ni a tà ọ́,

láìsanwó ni a ó sì rà ọ́ padà."

4 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.

"Ní ìgbà àkọ́kọ́ àwọn ènìyàn mi sọ̀kalẹ̀

lọ sí Ejibiti láti gbé;

láìpẹ́ ni Asiria pọ́n wọn lójú.

5 "Àti ní àkókò yìí, kí ni mo ní níbí?" ni Olúwa wí.

"Nítorí a ti kó àwọn ènìyàn mi lọ lọ́fẹ̀ẹ́,

àwọn tí ó sì ń jẹ ọba lórí wọn fi wọ́n ṣẹlẹ́yà,"

ni Olúwa wí.

"Àti ní ọjọọjọ́

orúkọ mi ni asọ̀rọ̀-òdì sí nígbà gbogbo.

6 Nítorí náà àwọn ènìyàn mi yóò mọ orúkọ mi;

nítorí ní ọjọ́ náà, wọn yóò mọ̀

pé, Èmi ni ó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀.

Bẹ́ẹ̀ ni, Èmi ni."

7 Báwo ni ó ṣe dára tó lórí òkè

ẹsẹ̀ àwọn tí ó mú ìyìnrere ayọ̀ wá,

tí wọ́n kéde àlàáfíà,

tí ó mú ìyìnrere wá,

tí ó kéde ìgbàlà,

tí ó sọ fún Sioni pé,

"Ọlọ́run rẹ ń jẹ ọba!"

8 Tẹ́tí sílẹ̀! Àwọn olùṣọ́ rẹ gbé ohùn wọn sókè

wọ́n kígbe papọ̀ fún ayọ̀.

Nígbà tí Olúwa padà sí Sioni,

wọn yóò rí i pẹ̀lú ojú u wọn.

9 Ẹ bú sí orin ayọ̀ papọ̀,

ẹ̀yin ahoro Jerusalẹmu,

nítorí Olúwa ti tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú,

ó sì ti ra Jerusalẹmu padà.

10 Olúwa yóò ṣí apá mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀

ní ojú gbogbo orílẹ̀-èdè,

àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò rí

ìgbàlà Ọlọ́run wa.

11 Ẹ túká, ẹ túká, ẹ jáde kúrò níhìn-ín yìí!

Ẹ má fọwọ́ kan ohun àìmọ́ kan!

Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ kí ẹ sì di mímọ́,

ẹ̀yin tí ẹ̀ ń gbé ohun èlò Olúwa.

12 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kì yóò yára kúrò

tàbí kí ẹ sáré lọ;

nítorí Olúwa ni yóò síwájú yín lọ,

Ọlọ́run Israẹli ni yóò sì ṣe ààbò lẹ́yìn ín yín.

Ìpọ́njú àti ògo ìránṣẹ́ náà

13 Kíyèsi i, ìránṣẹ́ mi yóò hùwà ọlọ́gbọ́n;

òun ni a ó gbé sókè tí a ó sì gbéga

a ó sì gbé e lékè gidigidi.

14 Gẹ́gẹ́ bí a ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ tí wọ́n ń bu ọlá fún un—

ìwò ojú rẹ ni a ti bàjẹ́ kọjá ti ẹnikẹ́ni àti ìrísí rẹ̀ ní a ti bàjẹ́ kọjá ohun tí ènìyàn ń fẹ́.

15 Bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe bomirin àwọn orílẹ̀-èdè ká,

àwọn ọba yóò sì pa ẹnu wọn mọ́ nítorí rẹ̀.

Nítorí ohun tí a kò sọ fún wọn, wọn yóò rí i,

àti ohun tí wọn kò tí ì gbọ́, ni yóò sì yé wọn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-