Publicidade

Isaías 56

Ìgbàlà fún àwọn mìíràn

1 Èyí ni ohun ti Olúwa sọ:

"Ẹ pa ìdájọ́ mọ́

ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà,

nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí

àti òdodo mi ni a ó fihàn láìpẹ́ jọjọ.

2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí,

àti fún ọmọ ènìyàn tí ó dìímú ṣinṣin,

tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́,

tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe."

3 Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀

mọ́ Olúwa sọ wí pé,

"Olúwa yóò yà mí sọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀."

Àti kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé,

"Igi gbígbẹ lásán ni mí."

4 Nítorí pé báyìí ni Olúwa wí:

"Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́,

tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi

tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin

5 fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹmpili àti àgbàlá rẹ̀

ìrántí kan àti orúkọ kan

tí ó sàn ju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin,

Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé

tí a kì yóò ké kúrò.

6 Àti àwọn àjèjì tí ó so ara wọn mọ́ Olúwa

láti sìn ín,

láti fẹ́ orúkọ Olúwa

àti láti foríbalẹ̀ fún un

gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́

àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—

7 àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi,

èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi.

Ẹbọ sísun wọn àti ìrúbọ wọn,

ni a ó tẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi;

nítorí a ó máa pe ilé mi ní

ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀-èdè."

8 Olúwa Olódùmarè sọ wí pé—

ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Israẹli jọ:

"Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lú wọn

yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kójọ."

Ẹ̀sùn tí Ọlọ́run fi kan àwọn ìkà

9 Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú pápá,

ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!

10 Àwọn olùṣọ́ Israẹli fọ́jú,

gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀;

gbogbo wọn jẹ́ adití ajá,

wọn kò lè gbó;

wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá,

wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.

11 Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀;

wọn kì í ní ànító.

Wọ́n jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn tí kò ní òye;

olúkúlùkù ń yà ṣọ́nà ara rẹ̀,

ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.

12 Igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn ni wí pé, "Wá, fún mi ní ọtí wáìnì!

Jẹ́ kí a mu ọtí líle wa lámu yó

ọ̀la yóò sì dàbí òní,

tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-