Publicidade

Isaías 35

Ayọ̀ àwọn ẹni ìràpadà

1 Aginjù àti ìyàngbẹ ilẹ̀ yóò yọ̀ fún wọn;

aginjù yóò ṣe àjọyọ̀ yóò sì kún fún ìtànná.

Gẹ́gẹ́ bí ewéko,

2 ní títanná yóò tanná;

yóò yọ ayọ̀ ńlá ńlá yóò sì kọrin.

Ògo Lebanoni ni a ó fi fún un,

ẹwà Karmeli àti Ṣaroni;

wọn yóò rí ògo Olúwa,

àti ẹwà Ọlọ́run wa.

3 Fún ọwọ́ àìlera lókun,

mú orúnkún tí ń yẹ̀ lókun.

4 Sọ fún àwọn oníbẹ̀rù ọkàn pé,

"Ẹ ṣe gírí, ẹ má bẹ̀rù;

Ọlọ́run yín yóò wá,

òun yóò wá pẹ̀lú ìgbẹ̀san;

pẹ̀lú ìgbẹ̀san mímọ́

òun yóò wá láti gbà yín là."

5 Nígbà náà ni a ó la ojú àwọn afọ́jú

àti etí àwọn odi kì yóò dákẹ́.

6 Nígbà náà ni àwọn arọ yóò máa fò bí àgbọ̀nrín,

àti ahọ́n odi yóò ké fún ayọ̀.

Odò yóò tú jáde nínú aginjù

àti àwọn odò nínú aṣálẹ̀.

7 Ilẹ̀ iyanrìn yíyan yóò di àbàtà,

ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ yóò di orísun omi.

Ní ibùgbé àwọn dragoni,

níbi tí olúkúlùkù dùbúlẹ̀,

ni ó jẹ́ ọgbà fún eèsún àti papirusi.

8 Àti òpópónà kan yóò wà níbẹ̀:

a ó sì máa pè é ní ọ̀nà ìwà mímọ́.

Àwọn aláìmọ́ kì yóò tọ ọ̀nà náà;

yóò sì wà fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà náà,

àwọn ìkà búburú kì yóò gba ibẹ̀ kọjá.

9 Kì yóò sí kìnnìún níbẹ̀,

tàbí kí ẹranko búburú kí ó dìde lórí i rẹ̀;

a kì yóò rí wọn níbẹ̀.

Ṣùgbọ́n àwọn ẹni ìràpadà nìkan ni yóò rìn níbẹ̀,

10 àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá.

Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin;

ayọ̀ ayérayé ni yóò dé wọn ní orí.

Ìdùnnú àti ayọ̀ ni yóò borí i wọn,

ìkorò àti ìtìjú yóò sì sá kúrò lọ́dọ̀ wọn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-