Publicidade

Isaías 24

Ìparun Olúwa lórí ilẹ̀ ayé

1 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun

gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé

yóò sì pa á run

òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́

yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—

2 bákan náà ni yóò sì rí

fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn,

fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀,

fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin,

fún olùtà àti olùrà,

fún ayáni àti atọrọ

fún ayánilówó àti onígbèsè.

3 Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá

a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run.

Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.

4 Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá,

ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un,

àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú

5 àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́;

wọ́n ti pa àwọn òfin run

wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà

wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.

6 Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run;

àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn.

Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù,

àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.

7 Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ,

gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.

8 Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́

ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró

ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.

9 Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́

ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.

10 Ìlú tí a run ti dahoro,

ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.

11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì

gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́,

gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.

12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro,

ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.

13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé

àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú,

gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi,

tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn

tí a kórè èso tán.

14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀;

láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo

ọláńlá Olúwa.

15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa;

gbé orúkọ Olúwa ga, àní

Ọlọ́run Israẹli,

ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun.

16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin;

"Ògo ni fún olódodo n nì."

Ṣùgbọ́n mo wí pé, "Mo ṣègbé, mo ṣègbé!

"Ègbé ni fún mi!

Alárékérekè dalẹ̀!

Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!"

17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́,

ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.

18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà

yóò ṣubú sínú ihò,

ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò

ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú.

Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀,

ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.

19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́

ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù,

a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.

20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí,

ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́;

ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù

tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.

21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà

gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run

àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.

22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀,

gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò,

a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú,

a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.

23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn;

nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba

ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu,

àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-