Publicidade

Isaías 50

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìgbọ́ràn ìránṣẹ́

1 Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

"Níbo ni ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ ìyá rẹ wà

èyí tí mo fi lé e lọ?

Tàbí èwo nínú àwọn olùyánilówó mi

ni mo tà ọ́ fún?

Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni a fi tà ọ́;

nítorí àìṣedéédéé rẹ ni a fi lé ìyá rẹ lọ.

2 Nígbà tí mo wá, èéṣe tí a kò fi rí ẹnìkan?

Nígbà tí mo pè, èéṣe tí kò fi sí ẹnìkan láti dáhùn?

Ọwọ́ mi a kúrú láti gbà ọ́?

Èmi kò ha ní agbára láti gbà ọ́ bí?

Nípa ìbáwí lásán, Èmi gbẹ omi òkun,

Èmi yí àwọn odò sí aṣálẹ̀;

àwọn ẹja wọn rà fún àìsí omi

wọ́n sì kú fún òǹgbẹ.

3 Èmi fi òkùnkùn bo sánmọ̀

mo sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ ṣe ìbòrí rẹ̀."

4 Olúwa Olódùmarè ti fún mi ni ahọ́n tí a fi iṣẹ́ rán,

láti mọ àwọn ọ̀rọ̀ tí ó lè gbé àwọn aláàárẹ̀ ró.

O jí mi láràárọ̀,

o jí etí mi láti gbọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹni tí à ń kọ́.

5 Olúwa Olódùmarè ti ṣí mi ní etí,

bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ṣọ̀tẹ̀ rí;

Èmi kò sì padà sẹ́yìn.

6 Mo ṣí ẹ̀yìn mi sílẹ̀ fún àwọn tí ó ń nà mí,

àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ mi fún àwọn tí ń fa irùngbọ̀n mi;

Èmi kò fi ojú mi pamọ́

kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́yà àti ìyọṣùtì sí.

7 Nítorí Olúwa Olódùmarè ràn mí lọ́wọ́,

a kì yóò dójútì mí.

Nítorí náà ni mo ṣe gbé ojú mi ró bí òkúta akọ

èmi sì mọ pé, ojú kò ní tì mí.

8 Ẹni tí ó dá mi láre wà nítòsí.

Ta ni ẹni náà tí yóò fẹ̀sùn kàn mí?

Jẹ́ kí a kojú ara wa!

Ta ni olùfisùn mi?

Jẹ́ kí ó kò mí lójú!

9 Olúwa Olódùmarè ni ó ń ràn mí lọ́wọ́.

Ta ni ẹni náà tí yóò dá mi lẹ́bi?

Gbogbo wọn yóò gbó bí aṣọ;

kòkòrò ni yóò sì jẹ wọn run.

10 Ta ni nínú yín tí ó bẹ̀rù Olúwa

tí ó sì ń gbọ́rọ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́nu?

Jẹ́ kí ẹni tí ń rìn ní òkùnkùn

tí kò ní ìmọ́lẹ̀,

kí ó gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa

kí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run rẹ̀.

11 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gbogbo ẹ̀yin ti ń tanná

tí ẹ sì ń fi pèsè iná ìléwọ́ fún ara yín,

ẹ lọ, kí ẹ sì máa rìn nínú ìmọ́lẹ̀ iná yín,

àti nínú ẹta iná tí ẹ ti dá.

Èyí ni yóò jẹ́ tiyín láti ọwọ́ mi wá.

Ẹ̀yin ó dùbúlẹ̀ nínú ìrora.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-