21 15.21-28: Mk 7.24-30. Jesu sì ti ibẹ̀ kúrò lọ sí Tire àti Sidoni. 22 Obìnrin kan láti Kenaani, tí ó ń gbé ibẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Ó ń bẹ̀bẹ̀, ó sì kígbe pé, "Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi; ọmọbìnrin mi ní ẹ̀mí èṣù ti ń dá a lóró gidigidi."
23 Ṣùgbọ́n Jesu kò fún un ní ìdáhùn, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì gbà á níyànjú pé, "Lé obìnrin náà lọ, nítorí ó ń kígbe tọ̀ wá lẹ́yìn."
24 15.24: Mt 10.6,23. Ó dáhùn pé, "Àgùntàn ilẹ̀ Israẹli tí ó nù nìkan ni a rán mi sí."
25 15.25: Mt 8.2; 18.26; 20.20; Jh 9.38. Obìnrin náà wá, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó bẹ̀bẹ̀ sí i pé, "Olúwa ṣàánú fún mi."
26 Ó sì dáhùn wí pé, "Kò tọ́ kí a gbé oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá."
27 Obìnrin náà sì wí pé, "Bẹ́ẹ̀ ni, síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ajá a máa jẹ èrúnrún tí ó ti orí tábìlì olówó wọn bọ́ sílẹ̀."
28 15.28: Mt 9.22,28; Mk 10.52; Lk 7.50; 17.19. Jesu sì sọ fún obìnrin náà pé, "Ìgbàgbọ́ ńlá ni tìrẹ! A sì ti dáhùn ìbéèrè rẹ." A sì mú ọmọbìnrin rẹ̀ láradá ní wákàtí kan náà.