20 Naomi sì dáhùn wí pé, "Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara,1.20 tí ó túmọ̀ sí, Ìkorò nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò. 21 Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?"