4 Ọba wí fún mi pé, "Kí ni ìwọ ń fẹ́?"
Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run, 5 mo sì dá ọba lóhùn pé, "Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́."