11 Nígbà náà ni ó béèrè lọ́wọ́ Jese pé, "Ṣé èyí ni gbogbo àwọn ọmọ rẹ?"
Jese dáhùn pé, "Ó ku àbíkẹ́yìn wọn, ó ń tọ́jú agbo àgùntàn."
Samuẹli sì wí pé, "Rán ìránṣẹ́ lọ pè é wá; àwa kò ní jókòó títí òun yóò fi dé."
12 Ó sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n sì mú un wọlé wá, ó jẹ́ ẹni tó mọ́ra, àwọ̀ ara rẹ̀ dùn ún wò, ó jẹ́ arẹwà gidigidi.
Nígbà náà ni Olúwa wí pé, "Dìde kí o sì fi òróró yàn án, òun ni ẹni náà."
13 Nígbà náà ni Samuẹli mú ìwo òróró, ó sì ta á sí i ní orí ní iwájú àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀, láti ọjọ́ náà lọ, Ẹ̀mí Mímọ́ Olúwa wá sí orí Dafidi nínú agbára. Samuẹli sì lọ sí Rama.