11 Olúwa sọ fún Mose pé, 12 "Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’ "
13 Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká. 14 Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀. 15 16.15: 1Kọ 10.3.Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, "Kí ni èyí?" Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe.
Mose sì wí fún wọn pé, "Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.