16 "Má ṣe bẹ̀rù," wòlíì náà dáhùn, "Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ."
17 Eliṣa sì gbàdúrà, "Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran." Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.