Orí àáké fò lójú omi
1 Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, "Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa. 2 Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé."
Ó sì wí pé, "Lọ."
3 Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, "Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?"
Eliṣa dá a lóhùn pé, "Èmi yóò lọ," 4 Ó sì lọ pẹ̀lú wọn.
Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi. 5 Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, "O! Olúwa mi, mo yá a ni!"
6 Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, "Níbo ni ó bọ́ sí?" Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi. 7 Ó wí pé, "Gbé e jáde." Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.