33 Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn. 34 Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
35 10.35: Sm 68.1,2. Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé,
"Dìde, Olúwa!
Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká,
kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ."
36 Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé,
"Padà, Olúwa,
sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli."