3 Wọ́n wí pé, ‘Èéṣe tí àwa fi ń gbààwẹ̀,
tí ìwọ kò sì tí ì rí?
Èéṣe tí àwa fi rẹra wa sílẹ̀,
tí ìwọ kò sì tí ì ṣe àkíyèsí?’
"Síbẹ̀síbẹ̀ ní ọjọ́ àwẹ̀ yín, ẹ̀yin ń ṣe bí ó ti wù yín
ẹ sì ń pọ́n àwọn òṣìṣẹ́ yín gbogbo lójú.
4 Àwẹ̀ yín sì parí nínú ìjà àti asọ̀,
àti lílu ọmọnìkejì ẹni pa pẹ̀lú ìkùùkuu.
Ẹ̀yin kò le è gbààwẹ̀ bí ẹ ti ń ṣe lónìí
kí ẹ sì retí kí a gbọ́ ohùn un yín ní ibi gíga.
5 Ǹjẹ́ èyí ha ni irú àwẹ̀ tí mo yàn bí,
ọjọ́ kan ṣoṣo fún ènìyàn láti rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀?
Ó ha jẹ pe kí ènìyàn tẹ orí rẹ̀ ba bí i koríko lásán ni bí
àti sísùn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú?
Ṣé ohun tí ẹ̀ ń pè ní àwẹ̀ nìyí,
ọjọ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa?
6 58.6: Ap 8.23. "Ǹjẹ́ irú àwẹ̀ tí mo ti yàn kọ́ ni èyí:
láti já gbogbo ẹ̀wọ̀n àìṣòdodo
àti láti tú gbogbo okùn àjàgà,
láti tú gbogbo àwọn ti à ń ni lára sílẹ̀
àti láti fọ́ gbogbo àjàgà?