Publicidade

Ezequiel 19

Orin ọfọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli

1 "Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli 2 wí pé:

" ‘Èwo nínú abo kìnnìún ni ìyá rẹ̀ ní àárín àwọn kìnnìún yòókù?

Ó sùn ní àárín àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.

3 Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára,

ó kọ́ ọ láti ṣọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.

4 Àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ nípa rẹ̀,

wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú iho wọn.

Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.

5 " ‘Nígbà tí abo kìnnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì jásí asán,

ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.

6 Ó sì ń rìn káàkiri láàrín àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára,

o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.

7 Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọn ìlú wọn di ahoro.

Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.

8 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè dìde sí i,

àwọn tó yìí ká láti ìgbèríko wá.

Wọn dẹ àwọ̀n wọn fún un,

wọn sì mú nínú ihò wọn.

9 Wọn fi ìwọ̀ gbé e sínú àgò, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli,

wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Israẹli.

10 " ‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀;

tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso,

ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.

11 Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lágbára tó láti fi ṣe ọ̀pá àṣẹ ìjòyè,

ó ga sókè láàrín ewé rẹ̀,

gíga rẹ̀ hàn jáde láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka rẹ̀.

12 Ṣùgbọ́n ó fà á tu ní ìrunú,

á sì wọ́ ọ lulẹ̀,

afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn sì gbé èso rẹ̀,

ọ̀pá líle rẹ̀ ti ṣẹ́, ó sì rọ

iná sì jó wọn run.

13 Báyìí, a tún ún gbìn sínú aṣálẹ̀

ni ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tó ń pòǹgbẹ omi.

14 Iná sì jáde láti ọ̀kan lára ẹ̀ka rẹ̀

ó sì pa ẹ̀ka àti èso rẹ̀ run,

dé bi pé kò sí ẹ̀ka tó lágbára lórí rẹ̀ mọ́;

èyí to ṣe fi ṣe ọ̀pá fún olórí mọ́.’

Èyí ni orin ọ̀fọ̀ a o sì máa lo bí orin ọ̀fọ̀."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-