Publicidade

Jeremias 20

14 Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi!

Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.

15 Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi,

tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé,

"A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!"

16 Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú

Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú

Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀,

ariwo ogun ní ọ̀sán.

17 Nítorí kò pa mí nínú,

kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi,

kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.

18 Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn,

láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀

àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-