Publicidade

Salmos 95

1 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa,

ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa.

2 Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́

kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò

orin àti ìyìn.

3 Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni,

ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.

4 Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà,

ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.

5 Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a

àti ọwọ́ rẹ̀ ni ó fi dá ìyàngbẹ ilẹ̀.

6 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín,

ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú

Olúwa ẹni tí ó dá wa,

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-