Publicidade

Salmos 27

Ti Dafidi.

1 Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi;

ta ni èmi yóò bẹ̀rù?

Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi,

ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?

2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi

láti jẹ ẹran-ara mi,

àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi,

wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.

3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi,

ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù;

bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi,

nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-