Publicidade

Salmos 96

1 Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa,

ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.

2 Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀

ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.

3 Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.

4 Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí;

òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.

5 Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè

ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.

6 Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀

agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.

7 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn,

ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.

8 Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un;

ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.

9 Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀;

ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-22_10-02-25-